Esra ORI 1 1 Ní ọdún kìn-ín-ní Kírúsì ọba Páṣíà, kí ọ̀rọ̀ Olúwa láti ẹnu Jeremáyà lè ṣẹ, Olúwa ru ẹ̀mí Kírúsì ọba Páṣíà sókè, tí ó fi kéde jákèjádò ìjọba rẹ̀, ó sì kọ ọ́ sínú ìwé pẹ̀lú pé, 2 Bayi ni Kirusi ọba Persia wi, Oluwa Ọlọrun ọrun ti fi gbogbo ijọba aiye fun mi; ó sì ti pàṣẹ fún mi láti kọ́ ilé fún òun ní Jérúsálẹ́mù ní Júdà. 3 Tani ninu nyin ninu gbogbo enia rẹ̀? Ọlọrun rẹ̀ ki o wà pẹlu rẹ̀, ki o si jẹ ki o gòke lọ si Jerusalemu, ti o wà ni Juda, ki o si kọ́ ile Oluwa Ọlọrun Israeli, (oun li Ọlọrun) ti o wà ni Jerusalemu. 4 Ati ẹnikẹni ti o kù ni ibikibi ti o ṣe atipo, jẹ ki awọn enia ipò rẹ̀ ràn a lọwọ pẹlu fadakà, ati wura, ati pẹlu ẹrù, ati pẹlu ẹran-ọ̀sin, pẹlu ọrẹ atinuwa fun ile Ọlọrun ti o wà ni Jerusalemu. 5 Nigbana li awọn olori awọn baba Juda ati Benjamini dide, ati awọn alufa, ati awọn ọmọ Lefi, pẹlu gbogbo awọn ti Ọlọrun ti gbe ẹmi wọn soke, lati gòke lọ lati kọ́ ile Oluwa ti o wà ni Jerusalemu. 6 Gbogbo àwọn tí wọ́n yí wọn ká sì fi ohun èlò fàdákà, wúrà, ẹrù àti ẹranko àti ohun iyebíye lọ́wọ́, yàtọ̀ sí gbogbo ohun tí wọ́n fi tinútinú fi rúbọ. 7. Ati Kirusi ọba si ko gbogbo ohun-elo ile Oluwa jade, ti Nebukadnessari ko jade lati Jerusalemu, ti o si ti fi wọn sinu ile awọn oriṣa rẹ̀; 8 Ani Kirusi ọba Persia mu jade lati ọwọ́ Mitredati, oluṣọ iṣura, o si kà wọn fun Ṣeṣbassari, olori Juda. 9 Èyí sì ni iye wọn: ọgbọ̀n àwo wúrà, ẹgbẹ̀rún àwo fàdákà, ọ̀bẹ mọ́kàndínlọ́gbọ̀n. 10 Ọgbọ̀n àwokòtò wúrà, àwo fadaka, irinwo ó lé mẹ́wàá, ati ẹgbẹrun (1,000) àwọn ohun èlò mìíràn. 11 Gbogbo ohun èlò wúrà àti fàdákà jẹ́ ẹgbàá mẹ́ta ó lé irinwo. Gbogbo wọnyi ni Ṣeṣbassari kó gòkè lọ pẹlu awọn igbekun ti a kó gòke lati Babiloni wá si Jerusalemu. ORI 2 1 NJẸ wọnyi li awọn ọmọ igberiko ti o gòke lati igbekun wá, ninu awọn ti a ti ko lọ, ti Nebukadnessari, ọba Babeli ti kó lọ si Babeli, ti o si tun pada wá si Jerusalemu ati Juda, olukuluku si ilu rẹ̀; 2 Ti o ba Serubbabeli wá: Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reeláyà, Mordekai, Bilṣani, Mispar, Bigfai, Rehumu, Baana. Iye àwọn ọkùnrin àwọn ọmọ Ísírẹ́lì: 3 Awọn ọmọ Paroṣi, ẹgbã o le mejilelãdọrin. 4 Awọn ọmọ Ṣefatiah ọrindinirinwo o le meji. 5 Awọn ọmọ Ara, ẹdẹgbẹrin o le marun. 6 Awọn ọmọ Pahati-moabu, ti awọn ọmọ Jeṣua ati Joabu, ẹgbẹrinla o le mejila. 7 Awọn ọmọ Elamu, ẹgbẹfa o le mẹrinlelãdọta. 8 Awọn ọmọ Satu, ẹdẹgbẹrin o le marun. 9 Awọn ọmọ Sakai, ẹdẹgbẹrin o le ọgọta. 10 Awọn ọmọ Bani, ẹgbẹta o le meji. 11 Awọn ọmọ Bebai, ẹgbẹta o le mẹta. 12 Awọn ọmọ Asgadi, ẹgbẹfa o le mejilelogun. 13 Awọn ọmọ Adonikamu, ẹgbẹta o le mẹfa. 14 Awọn ọmọ Bigfai, ẹgbã o le mẹrindilọgọta. 15 Awọn ọmọ Adini ãdọtalelẹgbẹrin o le mẹrin.
16 Awọn ọmọ Ateri ti Hesekiah, mejidilọgọrun. 17 Awọn ọmọ Besai, ọ̃dunrun o le mẹta. 18 Awọn ọmọ Jora, mejila. 19 Awọn ọmọ Haṣumu, igba o le mẹtalelogun. 20 Awọn ọmọ Gibbari, marundilọgọrun. 21 Awọn ọmọ Betlehemu, mẹtalelọgọfa. 22 Awọn ọkunrin Netofa, mẹrindilọgọta. 23 Awọn ọkunrin Anatoti, mejidilọgọfa. 24 Awọn ọmọ Asmafeti, mejilelogoji. 25 Awọn ọmọ Kirjatarimu, Kefira, ati Beeroti, ẹdẹgbẹrin o le mẹta. 26 Awọn ọmọ Rama ati Gaba, ẹgbẹta o le mọkanlelogun. 27 Awọn ọkunrin Mikmasi, mejilelọgọfa. 28 Awọn ọkunrin Beteli ati Ai, igba o le mẹtalelogun. 29 Awọn ọmọ Nebo, mejilelãdọta. 30 Awọn ọmọ Magbiṣi, ãdọtalelẹgbẹjọ. 31 Awọn ọmọ Elamu keji, ẹgbẹfa o le mẹrinlelãdọta. 32 Awọn ọmọ Harimu, ọrindinirinwo. 33 Awọn ọmọ Lodi, Hadidi, ati Ono, ẹdẹgbẹrin o le marun. 34 Awọn ọmọ Jeriko, irinwo o le marun. 35 Awọn ọmọ Senaah, ọkẹ mẹta o le 33. 36 Awọn alufa: awọn ọmọ Jedaiah, ti ile Jeṣua, ẹ̃dẹgbẹrun o din mẹtala. 37 Awọn ọmọ Immeri, ãdọtalelẹgbẹfa o le meji. 38 Awọn ọmọ Paṣuri, ẹgbẹfa o le meje. 39 Awọn ọmọ Harimu, ẹgbẹrun o le mẹtadilogun. 40 Awọn ọmọ Lefi: awọn ọmọ Jeṣua ati Kadmieli, ninu awọn ọmọ Hodafiya, mẹrinlelãdọrin. 41 Awọn akọrin: awọn ọmọ Asafu, mejidilọgọfa. 42 Awọn ọmọ awọn adena: awọn ọmọ Ṣallumu, awọn ọmọ Ateri, awọn ọmọ Talmoni, awọn ọmọ Akubu, awọn ọmọ Hatita, awọn ọmọ Ṣobai, gbogbo rẹ̀ jẹ mọkandilọgbọ̀n. 43 Awọn Netinimu: awọn ọmọ Siha, awọn ọmọ Hasufa, awọn ọmọ Taboti; 44 Awọn ọmọ Kerosi, awọn ọmọ Siaha, awọn ọmọ Padoni; 45 Awọn ọmọ Lebana, awọn ọmọ Hagaba, awọn ọmọ Akubu; 46 Awọn ọmọ Hagabu, awọn ọmọ Ṣalmai, awọn ọmọ Hanani; 47 Awọn ọmọ Gideli, awọn ọmọ Gahari, awọn ọmọ Reaiah; 48 Awọn ọmọ Resini, awọn ọmọ Nekoda, awọn ọmọ Gassamu; 49 Awọn ọmọ Ussa, awọn ọmọ Pasea, awọn ọmọ Besai; 50 Awọn ọmọ Asna, awọn ọmọ Mehunimu, awọn ọmọ Nefusimu; 51 Awọn ọmọ Bakbuku, awọn ọmọ Hakufa, awọn ọmọ Harhuri; 52 Awọn ọmọ Baslutu, awọn ọmọ Mehida, awọn ọmọ Harṣa; 53 Awọn ọmọ Barkosi, awọn ọmọ Sisera, awọn ọmọ Tama; 54 Awọn ọmọ Nesaya, awọn ọmọ Hatifa. 55 Awọn ọmọ awọn iranṣẹ Solomoni: awọn ọmọ Sotai, awọn ọmọ Sofereti, awọn ọmọ Perúda; 56 Awọn ọmọ Jaala, awọn ọmọ Darkoni, awọn ọmọ Gideli; 57 Awọn ọmọ Ṣefatiah, awọn ọmọ Hattili, awọn ọmọ Pokereti ti Sebaimu, awọn ọmọ Ami. 58 Gbogbo awọn Netinimu, ati awọn ọmọ awọn iranṣẹ Solomoni, jẹ ọdunrun o din mejila. 59 Wọnyi si li awọn ti o gòke lati Telmela, Telharsa, Kerubu, Addani, ati Immeri: ṣugbọn nwọn kò le fi ara ile baba wọn hàn, ati iru-ọmọ wọn, bi ọmọ Israeli ni nwọn iṣe. 60 Awọn ọmọ Delaiah, awọn ọmọ Tobiah, awọn ọmọ Nekoda, ãdọtalelẹgbẹta o le meji.