Skip to main content

Yoruba - The Book of 1st Kings

Page 1

1 Ọba ORI 1 1 NIGBATI Dafidi ọba si gbó, o si pọ̀ li ọjọ́; nwọn si fi aṣọ bò o, ṣugbọn kò gbóná. 2 Nitorina awọn iranṣẹ rẹ̀ wi fun u pe, Jẹ ki a wá ọdọmọbinrin wundia kan fun oluwa mi ọba: jẹ ki o duro niwaju ọba, ki o si ma ṣìna rẹ̀, ki o si dubulẹ li aiya rẹ, ki oluwa mi ọba ki o le mu õru. 3 Bẹ̃ni nwọn wá ọmọbinrin arẹwà kan ni gbogbo àgbegbe Israeli, nwọn si ri Abiṣagi, ara Ṣunemu, nwọn si mu u tọ̀ ọba wá. 4 Ọmọbinrin na si ṣe arẹwa gidigidi, o si nkẹ́ ọba, o si nṣe iranṣẹ fun u: ṣugbọn ọba kò mọ̀ ọ. 5 Nigbana ni Adonijah ọmọ Haggiti gbe ara rẹ̀ ga, wipe, Emi o jọba: o si pese kẹkẹ́ ati ẹlẹṣin fun u, ati ãdọta ọkunrin lati ma sare niwaju rẹ̀. 6 Baba rẹ̀ kò si bí i ninu ri nigba kan ri pe, Ẽṣe ti iwọ fi ṣe bẹ̃? òun náà sì jẹ́ arẹwà ọkùnrin; ìyá rẹ̀ sì bí i lẹ́yìn Ábúsálómù. 7 O si ba Joabu, ọmọ Seruiah, ati Abiatari, alufa gbìmọ: nwọn si tẹle Adonijah, ràn a lọwọ. 8 Ṣugbọn Sadoku alufaa, ati Benaiah ọmọ Jehoiada, ati Natani woli, ati Ṣimei, ati Rei, ati awọn ọkunrin alagbara ti Dafidi, kò si pẹlu Adonijah. 9 Adonija si pa agutan, ati malu, ati ẹran-ọ̀sin ti o sanra, lẹba okuta Soheleti, ti mbẹ leti En-rogeli, o si pè gbogbo awọn arakunrin rẹ̀ awọn ọmọ ọba, ati gbogbo awọn ọkunrin Juda, awọn iranṣẹ ọba: 10 Ṣugbọn Natani woli, ati Benaiah, ati awọn ọkunrin alagbara, ati Solomoni arakunrin rẹ̀, li on kò pè. 11 Nitorina Natani si wi fun Batṣeba iya Solomoni pe, Iwọ kò ti gbọ́ pe Adonijah ọmọ Haggiti jọba, Dafidi oluwa wa kò si mọ̀? 12 Njẹ nisisiyi wá, emi bẹ̀ ọ, jẹ ki emi fun ọ ni ìmọ, ki iwọ ki o le gba ẹmi ara rẹ là, ati ẹmi Solomoni ọmọ rẹ. . ẽṣe ti Adonijah fi jọba? 14 Kiyesi i, nigbati iwọ ba mba ọba sọ̀rọ nibẹ̀, emi pẹlu yio wọle tọ̀ ọ wá, emi o si fi idi ọ̀rọ rẹ mulẹ. 15 Batṣeba si wọle tọ̀ ọba lọ sinu iyẹwu: ọba si gbó; Abiṣagi ará Ṣunemu sì ṣe ìránṣẹ́ fún ọba. 16 Batṣeba si tẹriba, o si tẹriba fun ọba. Ọba si wipe, Kini iwọ nfẹ? 17 On si wi fun u pe, Oluwa mi, iwọ fi OLUWA Ọlọrun rẹ bura fun iranṣẹbinrin rẹ, wipe, Nitõtọ Solomoni ọmọ rẹ ni yio jọba lẹhin mi, on o si joko lori itẹ́ mi. 18 Njẹ nisisiyi, kiyesi i, Adonijah jọba; Njẹ nisisiyi, oluwa mi ọba, iwọ kò mọ̀. 19 Ó sì ti pa màlúù àti màlúù tí ó sanra àti àgùntàn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, ó sì pe gbogbo àwọn ọmọ ọba, Ábíátarì àlùfáà, àti Jóábù olórí ogun: ṣùgbọ́n Sólómónì ìránṣẹ́ rẹ ni kò pè. 20 Ati iwọ, oluwa mi, ọba, oju gbogbo Israeli mbẹ lara rẹ, ki iwọ ki o le sọ fun wọn ẹniti yio joko lori itẹ oluwa mi ọba lẹhin rẹ̀. 21 Bi bẹ̃kọ, nigbati oluwa mi ọba ba sùn pẹlu awọn baba rẹ̀, a o si kà emi ati Solomoni ọmọ mi si ẹlẹṣẹ. 22 Si kiyesi i, bi o ti mba ọba sọ̀rọ lọwọ, Natani woli si wọle pẹlu. 23 Nwọn si sọ fun ọba pe, Wò Natani woli. Nigbati o si wọle niwaju ọba, o tẹriba niwaju ọba, o doju rẹ̀ bolẹ.

24 Natani si wipe, Oluwa mi, ọba, iwọ ha wipe, Adonijah ni yio jọba lẹhin mi, on o si joko lori itẹ mi? 25 Nítorí ó ti sọ̀kalẹ̀ lọ lónìí, ó sì ti pa màlúù àti màlúù tí ó sanra àti àgùntàn ní ọ̀pọ̀lọpọ̀, ó sì pe gbogbo àwọn ọmọkùnrin ọba àti àwọn olórí ogun àti Ábíátarì àlùfáà; si kiyesi i, nwọn njẹ, nwọn si nmu niwaju rẹ̀, nwọn si wipe, Ki Adonija ọba ki o pẹ́. 26 Ṣugbọn emi, ani emi iranṣẹ rẹ, ati Sadoku alufa, ati Benaiah ọmọ Jehoiada, ati Solomoni iranṣẹ rẹ, ni kò pè. 27 Nkan yi ha ṣe lati ọwọ oluwa mi ọba, ti iwọ kò si fi i hàn iranṣẹ rẹ, ti yio joko lori itẹ oluwa mi ọba lẹhin rẹ̀? 28 Nigbana ni Dafidi ọba dahùn o si wipe, Pe Batṣeba fun mi. On si wá siwaju ọba, o si duro niwaju ọba. 29 Ọba si bura, o si wipe, Bi Oluwa ti wà, ti o ti rà ọkàn mi pada ninu gbogbo ipọnju; 30 Ani gẹgẹ bi mo ti fi Oluwa Ọlọrun Israeli bura fun ọ, wipe, Nitõtọ Solomoni ọmọ rẹ ni yio jọba lẹhin mi, yio si joko lori itẹ mi ni ipò mi; ani bẹ̃li emi o ṣe li ọjọ yi nitõtọ. 31 Nigbana ni Batṣeba wolẹ, o si bọ̀wọ̀ fun ọba, o si wipe, Ki Oluwa mi, Dafidi ọba ki o yè lailai. 32 Dafidi ọba si wipe, Ẹ pè Sadoku alufa fun mi, ati Natani woli, ati Benaiah ọmọ Jehoiada. Nwọn si wá siwaju ọba. 33 Ọba si wi fun wọn pe, Ẹ mu awọn iranṣẹ oluwa nyin pẹlu nyin, ki ẹ si mu Solomoni ọmọ mi ki o gùn ibaka mi, ki ẹ si mu u sọkalẹ wá si Gihoni. 34 Ki Sadoku alufa, ati Natani woli, fi ororo yàn a nibẹ̀ li ọba Israeli: ẹ si fun ipè, ki ẹ si wipe, Ki Solomoni ọba ki o pẹ. 35 Nigbana li ẹnyin o gòke tọ̀ ọ lẹhin, ki o le wá, ki o si joko lori itẹ́ mi; nitori on ni yio jẹ ọba ni ipò mi: emi si ti yàn a lati ṣe olori Israeli ati lori Juda. 36 Benaiah ọmọ Jehoiada si da ọba lohùn, o si wipe, Amin: Oluwa Ọlọrun Oluwa mi ọba wi bẹ̃ pẹlu. 37 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà pẹ̀lú olúwa mi ọba, bẹ́ẹ̀ náà ni kí ó rí pẹ̀lú Sólómónì, kí ó sì mú ìtẹ́ rẹ̀ tóbi ju ìtẹ́ Olúwa mi Dáfídì Ọba lọ. 38 Bẹ̃ni Sadoku alufa, ati Natani woli, ati Benaiah, ọmọ Jehoiada, ati awọn ara Kereti, ati awọn ara Peleti, sọkalẹ, nwọn si mu Solomoni gùn ibãka Dafidi ọba, nwọn si mu u wá si Gihoni. 39 Sádókù àlùfáà sì mú ìwo òróró kan láti inú àgọ́ náà wá, ó sì ta òróró sí Sólómónì. Nwọn si fun ipè; gbogbo enia si wipe, Ki Solomoni ọba ki o pẹ. 40 Gbogbo enia si gòke tọ̀ ọ lẹhin, awọn enia si fun fère, nwọn si yọ̀ pẹlu ayọ̀ nla, tobẹ̃ ti ilẹ fi nfọ̀ fun ariwo wọn. 41 Àdóníjà àti gbogbo àwÈn àwÈn àlejò tí wÊn wá pÆlú rÆ sì gbÊ bí wÊn ti parí jíjÅ. Nigbati Joabu si gbọ́ iró ipè, o si wipe, Ẽṣe ti ariwo ilu yi? 42 Bí ó ti ń sọ̀rọ̀ lọ́wọ́, Jonatani, ọmọ Abiatari, alufaa, dé. nitori akọni enia ni iwọ, iwọ si mu ihin rere wá. 43 Jonatani si dahùn o si wi fun Adonijah pe, Lõtọ, Oluwa wa, Dafidi ọba, ti fi Solomoni jọba. 44 Ọba si ti rán Sadoku alufa, ati Natani woli, ati Benaiah ọmọ Jehoiada, ati awọn ara Kereti, ati awọn ara Peleti pẹlu rẹ̀, nwọn si ti mu u gùn ibãka ọba. 45 Sádókù àlùfáà àti Nátánì wòlíì sì ti fi òróró yàn án ní ọba ní Gíhónì: wọ́n sì ti ibẹ̀ gòkè wá pẹ̀lú ayọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ìlú náà sì hó. Eyi ni ariwo ti o ti gbọ. 46 Ati pẹlu Solomoni joko lori itẹ ijọba. 47 Ati pẹlupẹlu awọn iranṣẹ ọba si wá lati sure fun Oluwa wa Dafidi ọba, wipe, Ki Ọlọrun ki o mu orukọ Solomoni ki o dara ju orukọ rẹ, ki o si mu itẹ rẹ tobi ju itẹ rẹ. Ọba si tẹriba lori akete.


Turn static files into dynamic content formats.

Create a flipbook
Yoruba - The Book of 1st Kings by Filipino Tracts and Literature Society Inc. - Issuu